Jump to content

Segun Awolowo

Lát'ọwọ́ Wikipedia, ìwé ìmọ̀ ọ̀fẹ́
Segun Awolowo

Ṣẹ́gun Awólọ́wọ̀
Ààrẹ National Trade Promotion Organisation
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
2021
PresidentJean-Claude Brou
Executive Director of the Nigerian Export Promotion Council
In office
February 2018 – November 2021
ÀàrẹMuhammadu Buhari
In office
November 2013 – November 2017
ÀàrẹGoodluck Jonathan
Muhammadu Buhari
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí
Olusegun Awolowo Jr.

27 Oṣù Kẹ̀sán 1963 (1963-09-27) (ọmọ ọdún 61)
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Education
ProfessionLawyer

Olúṣẹ́gun Awólọ́wọ̀ Jr. (wọ́n bí i ní 27 September 1963), jẹ́ agbẹjọ́rò ọmọ nàìjíríà, ó jẹ́ Alákòóso Àgbà fún Nigerian Export Promotion Council, láti ọdún 2013 dé ọdún 2021 .[1][2]. Ó jẹ́ ọmọ-ọmọ àgbà Olóṣèlù Nàìjíríà nnì, Olóyè Obafemi Awolowo .[3] Ní oṣù keje ọdún 2021, wọ́n panupọ̀ dìbò yàn-án gẹ́gẹ́ bí i ààrẹ àwọn àjọ tóń ṣe ìgbélárugẹ fún òwò ní orílẹ̀ èdè yìí (TPOs) láti ara ECOWAS member States.[4][5]

Ìbẹ̀rẹ̀ Ayé Rẹ̀

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]

Wọ́n bí Awólọ́wọ̀ ní 27 September 1963, bàbá rẹ̀ (Ṣẹ́gun Awólọ́wọ̀ Sr.) kú ní 1965 ní ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n láti ara ìjàm̀bá ọkọ̀ ní òpópó márosẹ̀ ìbàdàn sí Èkó àtijọ́ [6] . Ẹ̀yìn oṣù méjì tí bàbá rẹ̀ kú ni wọ́n bí i [7], ọ̀dọ̀ Ẹ̀gbọ́n Bàbá rẹ̀ ni ó gbé ka ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀, Abilékọ Tola Oyediran (nee Awolowo) àti ọkọ rẹ̀, Ọ̀jọ̀gbọ́n Kayode Oyediran. Kí ó tó dìgbà náà, ó gbé lọ́dọ̀ ìyá rẹ̀ àti àwọn tòun ti àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ̀.[8]

Awólọ́wọ̀ bẹ̀rẹ̀ ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Mayhill Convent School tòun ti Dolapo Osinbajo, ìyàwó igbákejì ààrẹ Yemi Osinbajo,lábẹ̀ àmójútó Ọ̀jọ̀gbọ́n àti Mrs Oyediran. láti ibẹ̀ , ó tẹ̀ síwájú lọ sí Igbobi College, Yaba, Ìpínlẹ̀ Èkó (Lagos State) fún ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírì tí ó sì parí ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírí rẹ̀ ní Government College, Ibadan. Lọ́gán tí ó parí ẹ̀kọ́ sẹ́kọ́ńdírì rẹ̀ ni ó tẹ̀síwájú lọ sí Ogun State University (now Olabisi Onabanjo University), Ago Iwoye tí ó sì kẹ́kọ̀ọ́ jáde pẹ̀lú oyè ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ LLB. [9]

Awolowo ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ilé iṣẹ́ amòfin Abayomi Sogbesan & Co. àti ilé iṣẹ́ amòfin ti GOK Ajayi & Co. lẹ́yìn ìgbà tí ó wọ àwùjọ àwọn agbẹjọ́rò ní oṣù kejìlá ọdún 1989. Ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìjọba President Olusegun Obasanjo's gẹ́gẹ́ bí Olùrànlọ́wọ́ Pàtàkì lórí àwọn ohun tó jẹ mọ́ àbàláyé, ètò àti ọ̀rọ̀ òfin. [10]

Ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ìjọba Umaru Musa Yar'Adua gẹ́gẹ́ bí Olùrànlọ́wọ́ Pàtàkì tí ó sì ṣiṣẹ́ ní agbègbè ìjọba Àpapọ̀ gẹ́gẹ́ bí i akọ̀wé fún ètò ìdàgbàsókè àwùjọ àti Akọ̀wé fún ètò ìrìnà ọkọ̀ láti 2007 di 2011. Ó padà sí ìdí iṣẹ́ òfin rẹ̀ lẹ́yìn ètò ìdìbò ọdún 2011 títí di 2013 tí Ààrẹ t Goodluck Jonathan yàn-án sí ipò Alákòóso àgbà fún ilé iṣẹ́ Nigerian Export Promotion Council[11] tí iṣẹ́ rẹ̀ sì tẹnubodò ní ọdún 2017, oṣù kọkànlá ṣùgbọ́n Ààrẹ Muhammadu Buhari tún tún-un yàn sí ipò yìí kan náà ní Oṣù kejì 2018 fún sáà ọdún mẹ́rin mìíràn.[12][13]

Awólọ́wọ̀ ní ìyàwó pẹ̀lú àwọn ọmọ. Ọmọbìnrin rẹ̀ Ṣeun jẹ́ ọlọ́rọ̀ ìyànjú tí ó sì ń darí ilé iṣẹ́ kan tí kìí ṣe ti ìjọba tí à ń pè ní Teach-A-Girl Nigeria. Èyí tí ó gbájú mọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ọmọbìnrin ní Nigeria. Òun yìí kan náà ni Òlùdásílẹ̀ Leads Africa àti 3D Living Moments.[14]

Àwọn Ìtọ́kasí

[àtúnṣe | àtúnṣe àmìọ̀rọ̀]
  1. Ehikioya, Augustine (26 September 2018). "Buhari greets Awolowo at 55". The Nation Online. https://thenationonlineng.net/buhari-greets-awolowo-at-55/. Retrieved 30 June 2019. 
  2. Usigbe, Leon (26 September 2018). "Buhari Greets Awolowo At 55". Tribune. Archived from the original on 30 June 2019. https://web.archive.org/web/20190630145327/https://tribuneonlineng.com/166062/. Retrieved 30 June 2019. 
  3. Babarinsa, Dare (25 November 2015). "The woman who gave us Awolowo". guardian.ng. Guardian. Archived from the original on 30 June 2019. https://web.archive.org/web/20190630003116/https://guardian.ng/opinion/the-woman-who-gave-us-awolowo/amp/. Retrieved 30 June 2019. 
  4. Anonymous (16 July 2021). "Buhari Congratulates Olusegun Awolowo On Election As President Of ECOWAS TPOs". Daily Trust. https://dailytrust.com/buhari-congratulates-olusegun-awolowo-on-election-as-president-of-ecowas-tpos. 
  5. "President Buhari Congratulates Olusegun Awolowo on Election to Lead Trade Promotion Organisations in West Africa". 16 July 2021. Archived from the original on 17 July 2021. Retrieved 7 December 2023. 
  6. Rilwan (18 July 2018). "Remembering Segun Awolowo". The Nation Newspaper. The Nation Newspaper. https://www.thenationonlineng.net/remembering-segun-awolowo/amp/. Retrieved 30 June 2019. 
  7. Lasisi, Akeem (25 July 2002). "Nigeria: Battle for Late Sage Obafemi Awolowo's Estate". All Africa. https://allafrica.com/stories/200207250357.html. Retrieved 30 June 2019. 
  8. Aworinde, Tobi (29 July 2018). "Years after dad's death, they would say he had gone to England – Segun Awolowo Snr's daughter, Funke". Punch Nigeria. https://www.punchng.com/years-after-dads-death-they-would-say-he-had-gone-to-england-segun-awolowo-snrs-daughter-funke/amp/. Retrieved 30 June 2019. 
  9. Aworinde, Tobi (29 July 2018). "Years after dad's death, they would say he had gone to England – Segun Awolowo Snr's daughter, Funke". Punch Nigeria. https://www.punchng.com/years-after-dads-death-they-would-say-he-had-gone-to-england-segun-awolowo-snrs-daughter-funke/amp/. Retrieved 30 June 2019. 
  10. "Olusegun Awolowo | NBASBL Conference 2019 .::. The 13th Annual Business Law Conference". www.nbasblconference.org. Archived from the original on 2019-07-04.  Unknown parameter |url-status= ignored (help)
  11. "Olusegun Awolowo - TradewithAfrica". 
  12. Press Release (28 February 2018). "Buhari reappoints Segun Awolowo as NEPC Chief Executive Officer". Premium Times. https://www.premiumtimesng.com/news/more-news/260137-buhari-reappoints-segun-awolowo-nepc-chief-executive-officer.html. Retrieved 30 June 2019. 
  13. Olowolagba, Fikayo (28 February 2018). "Buhari re-appoints Segun Awolowo as NEPC boss". Daily Post. https://dailypost.ng/2018/02/28/buhari-re-appoints-segun-awolowo-nepc-boss/. Retrieved 30 June 2019. 
  14. Anonymous (2 March 2019). "Segun Awolowo picks new date for daughter's wedding". Sun Newspaper. https://www.sunnewsonline.com/segun-awolowo-picks-new-date-for-daughters-wedding/. Retrieved 30 June 2019.